25. Àwọn ọmọ Israẹli gba gbogbo ìlú àwọn ará Amori, Heṣiboni ati àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè rẹ̀, wọ́n sì ń gbé inú wọn.
26. Heṣiboni ni olú ìlú Sihoni, ọba àwọn ará Amori. Ọba yìí ni ó bá ọba Moabu jà, ó sì gba ilẹ̀ rẹ̀ títí dé odò Arinoni.
27. Ìdí èyí ni àwọn akọrin òwe ṣe ń kọrin pé:“Wá sí Heṣiboni!Jẹ́ kí á tẹ ìlú ńlá Sihoni dó,kí á sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.
28. Ní àkókò kan, láti ìlú Heṣiboni,àwọn ọmọ ogun Sihoni jáde lọ bí iná;wọ́n run ìlú Ari ní Moabu,ati àwọn oluwa ibi gíga Arinoni.
29. Ẹ̀yin ará Moabu, ẹ gbé! Ẹ di ẹni ìparun, ẹ̀yin ọmọ oriṣa Kemoṣi!Ó ti sọ àwọn ọmọkunrin yín di ẹni tí ń sálọ fún ààbò;ó sì sọ àwọn ọmọbinrin yín di ìkógunfún Sihoni ọba àwọn ará Amori.
30. Ṣugbọn nisinsinyii, a ti pa ìrandíran wọn run,láti Heṣiboni dé Diboni,láti Naṣimu dé Nofa lẹ́bàá Medeba.”