Jeremaya 31:20-26 BIBELI MIMỌ (BM)

20. “Ṣé ọmọ mi ọ̀wọ́n ni Efuraimu ni?Ṣé ọmọ mi àtàtà ni?Nítorí bí mo tí ń sọ̀rọ̀ ibinu sí i tó, sibẹ mò ń ranti rẹ̀,nítorí náà ọkàn rẹ̀ ń fà mí;dájúdájú n óo ṣàánú rẹ̀.

21. Ẹ ri òpó mọ́lẹ̀ lọ fún ara yín,ẹ sàmì sí àwọn ojú ọ̀nà.Ẹ wo òpópónà dáradára, ẹ fiyèsí ọ̀nà tí ẹ gbà lọ.Ẹ yipada, ẹ̀yin ọmọ Israẹli,ẹ pada sí àwọn ìlú yín wọnyi.

22. Ìgbà wo ni ẹ óo ṣe iyèméjì dà, ẹ̀yin alainigbagbọ wọnyi?Nítorí OLUWA ti dá ohun titun sórí ilẹ̀ ayé,bíi kí obinrin máa dáàbò bo ọkunrin.”

23. OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, “Lẹ́ẹ̀kan sí i, wọn yóo tún máa lo gbolohun yìí ní ilẹ̀ Juda ati ní àwọn ìlú rẹ̀, nígbà tí mo bá dá ire wọn pada, wọn óo máa wí pé,‘OLUWA yóo bukun ọ, ìwọ òkè mímọ́ Jerusalẹmu,ibùgbé olódodo.’

24. Àwọn eniyan yóo máa gbé àwọn ìlú Juda ati àwọn agbègbè rẹ̀ pẹlu àwọn àgbẹ̀ ati àwọn darandaran.

25. Nítorí pé n óo fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní agbára; n óo sì tu gbogbo ọkàn tí ń kérora lára.”

26. Lẹ́sẹ̀ kan náà mo tají, mo wò yíká, oorun tí mo sùn sì dùn mọ́ mi.

Jeremaya 31