Orin Dafidi 132:9-18 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Jẹ́ kí àwọn alufaa rẹ wọ ẹ̀wù òdodo,kí àwọn eniyan mímọ́ rẹ sì máa kọrin ayọ̀.

10. Nítorí ti Dafidi, iranṣẹ rẹ,má jẹ́ kí ẹni tí a fi òróró rẹ yàn yíjú kúrò lára rẹ.

11. OLUWA ti ṣe ìbúra tí ó dájú fún Dafidi,èyí tí kò ní yipada; ó ní,“Ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹni n óo gbé ka orí ìtẹ́ rẹ.

12. Bí àwọn ọmọ rẹ bá pa majẹmu mi mọ́,tí wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí n óo fi lélẹ̀ fún wọn,àwọn ọmọ tiwọn náà óo jókòó lórí ìtẹ́ rẹ títí lae.”

13. Nítorí OLUWA ti yan Sioni;ó fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀:

14. Ó ní, “Ìhín ni ibi ìsinmi mi títí lae,níhìn-ín ni n óo máa gbé, nítorí pé ó wù mí.

15. N óo bù sí oúnjẹ rẹ̀ lọpọlọpọ;n óo fi oúnjẹ tẹ́ àwọn aláìní ibẹ̀ lọ́rùn.

16. N óo gbé ẹ̀wù ìgbàlà wọ àwọn alufaa rẹ̀,àwọn eniyan mímọ́ rẹ̀ yóo sì kọrin ayọ̀.

17. Níbẹ̀ ni n óo ti fún Dafidi ní agbára;mo ti gbé àtùpà kalẹ̀ fún ẹni tí mo fi òróró yàn.

18. N óo da ìtìjú bo àwọn ọ̀tá rẹ̀ bí aṣọ,ṣugbọn adé orí rẹ̀ yóo máa tàn yinrinyinrin.”

Orin Dafidi 132