6. Juda yóo rí ìgbàlà ní ìgbà tirẹ̀, Israẹli yóo sì wà láìléwu. Orúkọ tí a óo máa pè é ni ‘OLUWA ni òdodo wa.’
7. “Nítorí náà àkókò kan ń bọ̀, tí wọn kò ní máa búra ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti mọ́,
8. ṣugbọn tí wọn yóo máa wí pé, ‘Ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ ilé Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá, ati gbogbo ilẹ̀ tí wọn kó wọn lẹ́rú lọ, tí ó sì mú wọn pada sí ilẹ̀ wọn.’ Wọn óo wá máa gbé orí ilẹ̀ wọn nígbà náà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
9. Ọkàn mi bàjẹ́ nítorí àwọn wolii,gbogbo ara mi ń gbọ̀n.Mo dàbí ọ̀mùtí tí ó ti mu ọtí yó,mo dàbí ẹni tí ọtí ń pa,nítorí OLUWA, ati nítorí ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10. Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún àgbèrè ẹ̀sìn,ọ̀nà ibi ni wọ́n ń tọ̀,wọn kò sì lo agbára wọn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́nítorí ègún, ilẹ̀ ti di gbígbẹgbogbo pápá oko ló ti gbẹ.
11. Ati wolii, ati alufaa, ìwà burúkú ni wọ́n ń hù,ní ilé mi pàápàá mo rí iṣẹ́ ibi wọn,èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
12. Nítorí náà ọ̀nà wọn yóo dàbí ọ̀nà tí ń yọ̀ ninu òkùnkùn,a óo tì wọ́n sinu rẹ̀, wọn yóo sì ṣubú,nítorí n óo mú kí ibi bá wọn ní ọdún ìjìyà wọn.
13. Mo rí nǹkankan tí ó burú lọ́wọ́ àwọn wolii Samaria:Ẹ̀mí oriṣa Baali ni wọ́n fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀;wọ́n sì ń ṣi àwọn ọmọ Israẹli, eniyan mi, lọ́nà.
14. Mo rí nǹkankan tí ó bani lẹ́rù lọ́wọ́ àwọn wolii Jerusalẹmu:Wọ́n ń ṣe àgbèrè ẹ̀sìn,wọ́n ń hùwà èké;wọ́n ń ran àwọn ẹni ibi lọ́wọ́,kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni yipada kúrò ninu iṣẹ́ ibi rẹ̀.Gbogbo wọn ti di ará Sodomu lójú mi,àwọn ará Jerusalẹmu sì dàbí àwọn ará Gomora.
15. Nítorí náà OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa àwọn wolii pé:N óo fún wọn ní ewé igi kíkorò jẹ,n óo fún wọn ní omi májèlé mu.Nítorí pé láti ọ̀dọ̀ àwọn wolii Jerusalẹmuni ìwà burúkú ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ yìí.
16. OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wolii tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fun yín, tí wọ́n ń mu yín gbẹ́kẹ̀lé irọ́. Ohun tí wọn fẹ́ lọ́kàn wọn ni wọ́n ń sọ, kì í ṣe ẹnu èmi OLUWA ni wọ́n ti gbọ́ ọ.
17. Wọ́n ń sọ lemọ́lemọ́ fún àwọn tí wọn kò ka ọ̀rọ̀ OLUWA sí pé, yóo dára fún wọn. Wọ́n ń wí fún gbogbo àwọn tí wọn ń tẹ̀lé àìgbọràn ọkàn wọn pé ibi kò ní bá wọn.”