Samuẹli Kinni 2:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Hana bá gbadura báyìí pé:“Ọkàn mi kún fún ayọ̀ ninu OLUWA,Ó sọ mí di alágbára;mò ń fi àwọn ọ̀tá mi rẹ́rìn-ín,nítorí mò ń yọ̀ pé OLUWA gbà mí là.

2. “Kò sí ẹni mímọ́ bíi OLUWA,kò sí ẹlòmíràn,àfi òun nìkan ṣoṣo.Kò sí aláàbò kan tí ó dàbí Ọlọrun wa.

3. Má sọ̀rọ̀ pẹlu ìgbéraga mọ́,má jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìgbéraga ti ẹnu rẹ jáde,nítorí Ọlọrun tí ó mọ ohun gbogbo ni OLUWA,gbogbo ohun tí ẹ̀dá bá ṣe ni ó sì máa ń gbéyẹ̀wò.

4. Ọrun àwọn alágbára dá,ṣugbọn àwọn aláìlágbára di alágbára.

5. Àwọn tí wọ́n rí oúnjẹ jẹ lájẹyó ríti di ẹni tí ń fi ara wọn ṣọfà nítorí oúnjẹ,ṣugbọn àwọn tí ebi ti ń pa tẹ́lẹ̀ rí tí ń jẹ àjẹyó.Àgàn ti di ọlọ́mọ meje,ọlọ́mọ pupọ ti di aláìní.

6. OLUWA ni ó lè pa eniyan tán,kí ó sì tún jí i dìde;òun ni ó lè múni lọ sinu isà òkú,tí ó sì tún lè fani yọ kúrò níbẹ̀.

7. OLUWA ni ó lè sọni di aláìní,òun náà ni ó sì lè sọ eniyan di ọlọ́rọ̀.Òun ni ó ń gbéni ga,òun náà ni ó sì ń rẹ eniyan sílẹ̀.

8. OLUWA ń gbé talaka dìde láti ipò ìrẹ̀lẹ̀;ó ń gbé aláìní dìde láti inú òṣì rẹ̀,láti mú wọn jókòó pẹlu àwọn ọmọ ọba,kí wọ́n sì wà ní ipò ọlá.Nítorí pé òun ni ó ni àwọn ìpìlẹ̀ ayé,òun ni ó sì gbé ayé kalẹ̀ lórí wọn.

9. “Yóo pa àwọn olóòótọ́ tí wọ́n jẹ́ tirẹ̀ mọ́,ṣugbọn yóo mú kí àwọn eniyan burúkú parẹ́ ninu òkùnkùn;nítorí pé, kì í ṣe nípa agbára eniyan, ni ẹnikẹ́ni lè fi ṣẹgun.

Samuẹli Kinni 2