Samuẹli Keji 22:37-46 BIBELI MIMỌ (BM)

37. Ìwọ ni o kò jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tá tẹ̀ mí,bẹ́ẹ̀ ni o kò jẹ́ kí ẹsẹ̀ mí kí ó yẹ̀.

38. Mo lépa àwọn ọ̀tá mi,mo sì ṣẹgun wọnn kò pada lẹ́yìn wọn títí tí mo fi pa wọ́n run.

39. Mo pa wọ́n run, mo bì wọ́n lulẹ̀;wọn kò sì lè dìde mọ́;wọ́n ṣubú lábẹ́ ẹsẹ̀ mi.

40. Ìwọ ni o fún mi lágbára láti jagun,o jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi rì lábẹ́ mi.

41. O mú kí àwọn ọ̀tá mi sá fún mi,mo sì pa àwọn tí wọ́n kórìíra mi run.

42. Wọ́n wá ìrànlọ́wọ́ káàkiri,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó lè gbà wọ́n;wọ́n pe OLUWA,ṣugbọn kò dá wọn lóhùn.

43. Mo fọ́ wọn túútúú, wọ́n sì dàbí erùpẹ̀ ilẹ̀;mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀, wọ́n sì dàbí ẹrọ̀fọ̀ lójú títì.

44. “Ìwọ ni o gbà mí lọ́wọ́ ìjà àwọn eniyan mi,o sì mú kí ìjọba mi dúró lórí àwọn orílẹ̀ èdè;àwọn eniyan tí n kò mọ̀ rí di ẹni tí ó ń sìn mí.

45. Àwọn àjèjì ń wólẹ̀ níwájú mi,ẹsẹ̀kẹsẹ̀ tí wọ́n bá ti gbúròó mi, ni wọ́n ń mú àṣẹ mi ṣẹ.

46. Ẹ̀rù ba àwọn àjèjì,wọ́n gbọ̀n jìnnìjìnnì jáde ní ibi ààbò wọn.

Samuẹli Keji 22