Orin Dafidi 73:6-9 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Nítorí náà, wọn á kó ìgbéraga bọ ọrùn bí ẹ̀gbà,wọn á fi ìwà ipá bora bí aṣọ.

7. Wọ́n sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú wọn yíbò;èrò òmùgọ̀ sì kún ọkàn wọn ní àkúnwọ́sílẹ̀.

8. Wọ́n ń pẹ̀gàn eniyan, wọ́n ń sọ̀rọ̀ pẹlu ìlara;wọ́n sì ń fi ìgbéraga halẹ̀.

9. Wọ́n ń fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ òdì sí Ọlọrun;wọn a sì máa sọ̀rọ̀ ìgbéraga káàkiri ayé.

Orin Dafidi 73