Orin Dafidi 45:5-10 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Àwọn ọfà rẹ mú, wọ́n gún àwọn ọ̀tá ọba lọ́kàn,àwọn eniyan ń wó lulẹ̀ níwájú rẹ.

6. Ìjọba tí Ọlọrun fún ọ wà lae ati laelae.Ọ̀pá àṣẹ rẹ, ọ̀pá àṣẹ ẹ̀tọ́ ni.

7. O fẹ́ràn òdodo, o sì kórìíra ìwà ìkànítorí náà ni Ọlọrun, àní Ọlọrun rẹ, ṣe fi àmì òróró yàn ọ́.Àmì òróró ayọ̀ ni ó fi gbé ọ gaju àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ lọ.

8. Aṣọ rẹ kún fún òórùn oríṣìíríṣìí turari,láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ni wọ́n tí ń fi ohun èlò ìkọrin olókùn dá ọ lára yá.

9. Àwọn ọmọ ọba wà lára àwọn obinrin inú àgbàlá rẹ,ayaba dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ,ó fi ojúlówó wúrà ṣe ọ̀ṣọ́ sára.

10. Gbọ́, ìwọ ọmọbinrin, ronú kí o sì tẹ́tí sílẹ̀,gbàgbé àwọn eniyan rẹ ati ilé baba rẹ;

Orin Dafidi 45