Orin Dafidi 107:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun,nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2. Kí àwọn tí OLUWA ti rà pada kí ó wí bẹ́ẹ̀,àní, àwọn tí ó yọ kúrò ninu ìpọ́njú,

3. tí ó kó wọn jáde kúrò láàrin àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì,láti ìhà ìlà oòrùn ati láti ìhà ìwọ̀ oòrùn,láti ìhà àríwá ati láti ìhà gúsù.

4. Àwọn kan ń káàkiri ninu aṣálẹ̀,wọn kò sì rí ọ̀nà dé ìlú tí wọ́n lè máa gbé.

5. Ebi pa wọ́n, òùngbẹ gbẹ wọ́n,ó sì rẹ̀ wọ́n wá láti inú.

Orin Dafidi 107