Nehemaya 3:19-22 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Eseri ọmọ Jeṣua, aláṣẹ Misipa, náà ṣe àtúnṣe apá kan lára ibi ihamọra ní ibi igun odi.

20. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Baruku, ọmọ Sabai, ṣe àtúnṣe láti apá ibi Igun odi títí dé ẹnu ọ̀nà ilé Eliaṣibu olórí alufaa.

21. Lẹ́yìn rẹ̀, Meremoti, ọmọ Uraya, ọmọ Hakosi, ṣe àtúnṣe apá tiwọn láti ẹnu ọ̀nà ilé Eliaṣibu títí dé òpin ilé Eliaṣibu.

22. Lẹ́yìn rẹ̀, àwọn alufaa, àwọn ará pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọdani ṣe àtúnṣe ọ̀dọ̀ tiwọn.

Nehemaya 3