Johanu 12:40-46 BIBELI MIMỌ (BM)

40. “Ojú wọn ti fọ́,ọkàn wọn sì ti le;kí wọn má baà fi ojú wọn ríran,kí òye má baà yé wọn.Kí wọn má baà yipada,kí n má baà wò wọ́n sàn.”

41. Aisaya sọ nǹkan wọnyi nítorí ó rí ògo Jesu, ó wá sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀.

42. Sibẹ ọpọlọpọ ninu àwọn aṣaaju gbà á gbọ́; ṣugbọn wọn kò jẹ́wọ́ nítorí wọ́n bẹ̀rù àwọn Farisi, kí wọn má baà yọ wọ́n kúrò ninu àwùjọ;

43. nítorí wọ́n fẹ́ràn ìyìn eniyan ju ìyìn Ọlọrun lọ.

44. Jesu bá kígbe pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, kì í ṣe èmi ni ó gbàgbọ́ bíkòṣe ẹni tí ó rán mi níṣẹ́.

45. Ẹni tí ó bá rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi.

46. Mo wá sinu ayé bí ìmọ́lẹ̀, kí ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́ má baà wà ninu òkùnkùn.

Johanu 12