Jeremaya 5:17-31 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Wọn yóo jẹ yín ní oúnjẹ,wọn yóo sì kó gbogbo ìkórè oko yín lọ,wọn yóo run àwọn ọmọ yín lọkunrin ati lobinrin.Wọn yóo run ẹran ọ̀sìn yín,ati àwọn mààlúù yín.Wọn yóo run èso ọgbà àjàrà yín, ati igi ọ̀pọ̀tọ́ yín.Idà ni wọn yóo fi pa àwọn ìlú olódi yín tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé run.”

18. OLUWA ní, “Ṣugbọn sibẹ, ní gbogbo àkókò yìí, n kò ní pa yín run patapata,

19. nígbà tí àwọn eniyan bá bèèrè pé, ‘Kí ló dé tí OLUWA Ọlọrun wa fi ṣe gbogbo nǹkan wọnyi sí wa?’ Ẹ óo le dá wọn lóhùn pé bí ẹ ṣe kọ èmi OLUWA sílẹ̀, tí ẹ sì ń bọ oriṣa àjèjì ní ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ẹ óo ṣe sin àwọn àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.”

20. OLUWA ní, “Kéde rẹ̀ ní ilẹ̀ Jakọbu,sì ṣe ìfilọ̀ rẹ̀ ní ilẹ̀ Juda:

21. Ẹ wá gbọ́, ẹ̀yin òmùgọ̀, aláìlọ́gbọ́n,ẹ̀yin tí ẹ lójú, ṣugbọn tí ẹ kò ríran;ẹ létí, ṣugbọn tí ẹ kò gbọ́ràn.

22. Ẹ̀rù mi kò tilẹ̀ bà yín?Èmi OLUWA ni mò ń bi yín léèrè.Ẹ wà níwájú mi ẹ kò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀.Èmi tí mo fi iyanrìn pààlà fún omi òkun,tí òkun kò sì gbọdọ̀ rékọjá rẹ̀ títí ayé!Bí ó tilẹ̀ ń ru sókè, kò lágbára kan,kí ìgbì rẹ̀ máa hó yaya, kò lè kọjá ààlà náà.

23. Ṣugbọn ọkàn ẹ̀yin eniyan wọnyi le, ọlọ̀tẹ̀ sì ni yín.Ẹ ti yapa, ẹ sì ti ṣáko lọ.

24. Ẹ kò sì rò ó lọ́kàn yín, kí ẹ wí pé:‘Ẹ jẹ́ kí á bẹ̀rù OLUWA Ọlọrun wa,tí ó ń fún wa ní òjò lákòókò rẹ̀,ati òjò àkọ́rọ̀ ati àrọ̀kẹ́yìn;OLUWA tí ó ń bá wa mú ọjọ́ ìkórè lọ́wọ́,tí kì í jẹ́ kí àsìkò ìkórè ó yẹ̀.’

25. Àìdára yín ti yí ìgbà wọnyi pada,ẹ̀ṣẹ̀ yín ti dínà ohun rere fun yín.

26. “Àwọn eniyan burúkú wà láàrin àwọn eniyan mi,wọ́n ń dọdẹ eniyan bí ẹni dọdẹ ẹyẹ,wọ́n dẹ tàkúté, wọ́n fi ń mú eniyan.

27. Ilé wọn kún fún ìwà ọ̀dàlẹ̀,bíi kùùkú tí ó kún fún ẹyẹ.Nítorí èyí, wọ́n di eniyan ńlá,wọ́n di olówó,

28. wọ́n sanra, ara wọn sì ń dán.Ṣugbọn iṣẹ́ ibi wọn kò ní ààlà.Wọn kìí dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ fún aláìníbaba,kí ó lè rí ẹ̀tọ́ rẹ̀ gbà;wọn kò sì jẹ́ gbèjà aláìní,kí wọ́n bá a dáàbò bo ẹ̀tọ́ rẹ̀ nílé ẹjọ́.

29. Ṣé n kò wá ní jẹ wọ́n níyà fún àwọn nǹkan tí wọ́n ṣe wọnyi?Kí n má gbẹ̀san ara mi, lára irú orílẹ̀-èdè yìí?

30. Nǹkan burúkú tó yani lẹ́nu,ní ń ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà:

31. Àwọn wolii ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké,àwọn alufaa ń sọ ọ̀rọ̀ èké àwọn wolii di òfin,àwọn eniyan mi sì fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀.Ṣugbọn kí ni wọ́n óo ṣe nígbà tí òpin bá dé?”

Jeremaya 5