16. Má sọkún mọ́, nu ojú rẹ nù,nítorí o óo jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.Àwọn ọmọ rẹ yóo pada wá láti ilẹ̀ ọ̀tá wọn.
17. Ìrètí ń bẹ fún ọ lẹ́yìn ọ̀la,àwọn ọmọ rẹ yóo pada sí orílẹ̀-èdè wọn.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
18. “Mo gbọ́ bí Efuraimu tí ń kẹ́dùn,ó ní: ‘O ti bá mi wí, ìbáwí sì dùn mí,bí ọmọ mààlúù tí a kò kọ́.Mú mi pada, kí n lè pada sí ààyè mi,nítorí pé ìwọ ni OLUWA, Ọlọrun mi.