Àwọn Ọba Kinni 11:39-43 BIBELI MIMỌ (BM)

39. Ó ní òun óo jẹ arọmọdọmọ Dafidi níyà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ Solomoni, ṣugbọn kò ní jẹ́ títí ayé.”

40. Nítorí ọ̀rọ̀ yìí, Solomoni ń wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣugbọn Jeroboamu sá lọ sọ́dọ̀ Ṣiṣaki, ọba Ijipti, níbẹ̀ ni ó sì wà títí tí Solomoni fi kú.

41. Àwọn nǹkan yòókù tí Solomoni ṣe: gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, ati ọgbọ́n rẹ̀, ni a kọ sinu Ìwé Ìṣe Solomoni.

42. Ogoji ọdún ni ó fi jọba lórí gbogbo Israẹli ní Jerusalẹmu.

43. Nígbà tí ó kú, wọ́n sin ín sí ìlú Dafidi, baba rẹ̀, Rehoboamu, ọmọ rẹ̀ sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

Àwọn Ọba Kinni 11