16. Kórà, Gátamù àti Ámálékì. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Élífásì ní Édómù wá, wọ́n jẹ́ ọmọ-ọmọ Ádà.
17. Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Rúélì,Náhátì, Ṣérátì, Ṣámò àti Mísà. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Rúélì jáde ní Édómù. Ọmọ-ọmọ Básémátì aya Ísọ̀ ni wọ́n jẹ́.
18. Àwọn ọmọ Óhólíbámà aya Ísọ̀:Jéúsì, Jálámì, àti Kórà, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olorí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Óhólíbámà ọmọ Ánà, ìyàwó Ísọ̀ wá.
19. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ísọ̀ (Édómù). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
20. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣéírì ara Hórì tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà:Lótanì, Ṣóbálì, Ṣíbéónì, Ánà
21. Dísónì, Éṣérì, àti Díṣánì, àwọn wọ̀nyìí ọmọ Ṣéírì ni Édómù.
22. Àwọn ọmọ Lótanì:Órì àti Ómámù: Arábìnrin Lótanì sì ni Tímínà.
23. Àwọn ọmọ Ṣóbálì:Álífánì, Mánáhátì, Ébálì, Ṣéfò àti Onámù.
24. Àwọn ọmọ Ṣíbéónì:Áíyà àti Ánà. Èyí ni Ánà tí ó rí ìṣun omi gbígbóná ní inú asálẹ̀ bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣébéónì baba rẹ̀.
25. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ánà:Dísónì àti Óhólíbámà (Àwọn ọmọbìnrin ni wọn).
26. Àwọn ọmọ Dísónì ni:Hémídánì, Ésíbánì, Ítíránì àti Kéránì.
27. Àwọn ọmọ Éṣérì:Bílíhánì, Ṣááfánì, àti Ákánì.
28. Àwọn ọmọ Díṣánì ni Húsì àti Áránì.
29. Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hórì:Lótanì, Ṣóbálì, Ṣíbéónì, Áná,
30. Dísónì Éṣérì, àti Díṣánì. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Órì gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Ṣéírì.
31. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọba tí ó ti jẹ ní Édómù kí ó tó di pé a ń jẹ ọba ní Ísírẹ́lì rárá:
32. Bẹ́là ọmọ Béórì jẹ ní Édómù. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Díníhábà.
33. Nígbà tí Bẹ́là kú, Jóbábù ọmọ Ṣérà ti Bósírà sì jọba ní ipò rẹ̀.
34. Nígbà tí Jóbábù kú, Úṣámù láti ilẹ̀ Témánì sì jọba ní ipò rẹ̀.
35. Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì tí ó ṣẹ́gun Mídíánì ní orílẹ̀ èdè Móábù sì jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì.