Jer 27:15-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Nitori emi kò rán wọn, li Oluwa wi, ṣugbọn nwọn nsọ asọtẹlẹ eke li orukọ mi: ki emi ki o lè lé nyin jade, ki ẹ ṣegbe, ẹnyin, pẹlu awọn woli ti o sọ asọtẹlẹ fun nyin.

16. Pẹlupẹlu emi sọ fun awọn alufa ati fun gbogbo enia yi wipe, Bayi li Oluwa wi, Ẹ má gbọ́ ọ̀rọ awọn woli ti nsọ asọtẹlẹ fun nyin wipe, Sa wò o, ohun-èlo ile Oluwa li a o mu pada li aipẹ nisisiyi lati Babeli wá: nitori nwọn sọ asọtẹlẹ eke fun nyin.

17. Ẹ máṣe gbọ́ ti wọn; ẹ sin ọba Babeli, ẹ si yè: ẽṣe ti ilu yi yio fi di ahoro?

18. Ṣugbọn bi nwọn ba ṣe woli, ati bi ọ̀rọ Oluwa ba wà pẹlu wọn, jẹ ki nwọn ki o bẹbẹ lọdọ Oluwa awọn ọmọ-ogun, ki ohun-èlo iyokù ni ile Oluwa ati ni ile ọba Judah, ati ni Jerusalemu, ki nwọn ki o máṣe lọ si Babeli.

19. Nitori bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi niti opó mejeji, ati niti agbada nla, ati niti ipilẹṣẹ, ati niti ohun-èlo iyokù ti o kù ni ilu yi.

20. Eyi ti Nebukadnessari, ọba Babeli, kò mu lọ nigbati o mu Jekoniah, ọmọ Jehoiakimu, ọba Juda, ni igbèkun lati Jerusalemu lọ si Babeli, pẹlu gbogbo awọn ọlọla Juda ati Jerusalemu;

21. Nitori bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun, Ọlọrun Israeli wi, niti ohun-èlo ti o kù ni ile Oluwa, ati ni ile ọba Juda ati Jerusalemu.

22. A o kó wọn lọ si Babeli, nibẹ ni nwọn o wà titi di ọjọ na ti emi o bẹ̀ wọn wò, li Oluwa wi, emi o si mu wọn goke wá, emi o si mu wọn pada wá si ibi yi.

Jer 27