Gẹn 25:14-19 Yorùbá Bibeli (YCE)

14. Ati Miṣma, ati Duma, ati Masa;

15. Hadari, ati Tema, Jeturi, Nafiṣi, ati Kedema:

16. Awọn wọnyi li awọn ọmọ Iṣmaeli, iwọnyi si li orukọ wọn, li ori-ori ilu wọn, li ori-ori ile odi wọn; ijoye mejila li orilẹ-ède wọn.

17. Iwọnyi si li ọdún aiye Iṣmaeli, ẹtadilogoje ọdún: o si jọwọ ẹmi rẹ̀ lọwọ, o si kú; a si kó o jọ pọ̀ pẹlu awọn enia rẹ.

18. Nwọn si tẹ̀dó lati Hafila lọ titi o fi de Ṣuri, ti o wà niwaju Egipti, bi iwọ ti nlọ sìha Assiria: o si kú niwaju awọn arakonrin rẹ̀ gbogbo.

19. Iwọnyi si ni iran Isaaki, ọmọ Abrahamu: Abrahamu bí Isaaki:

Gẹn 25