Orin Dafidi 89:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. ‘N óo fi ìdí àwọn ọmọ rẹ múlẹ̀ títí lae,n óo sì gbé ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

5. Jẹ́ kí ojú ọ̀run máa kọrin ìyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ, OLÚWA;kí àwọn eniyan mímọ́ sì máa kọrin ìyìn òtítọ́ rẹ.

6. Nítorí ta ni a lè fi wé ọ ní ọ̀run, OLUWA?Ta ni ó dàbí OLUWA láàrin àwọn ẹ̀dá ọ̀run?

7. Ọlọrun, ìwọ ni a bẹ̀rù ninu ìgbìmọ̀ àwọn eniyan mímọ́,o tóbi, o sì lẹ́rù ju gbogbo àwọn tí ó yí ọ ká lọ?

Orin Dafidi 89