54. Ó kó wọn wá sí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀,sí orí òkè tí ó ti fi agbára rẹ̀ gbà.
55. Ó lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde kí wọn ó tó dé ibẹ̀;ó pín ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn bí ohun ìní;ó sì fi àwọn ọmọ Israẹli jókòó ninu àgọ́ wọn.
56. Sibẹ, wọ́n dán Ọ̀gá Ògo wò, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí i;wọn kò tẹ̀lé ìlànà rẹ̀.
57. Wọ́n yipada, wọ́n sì hu ìwà ọ̀dàlẹ̀bíi ti àwọn baba ńlá wọn;wọn kò ṣe é gbẹ́kẹ̀lé, wọ́n dàbí ọfà tí ó tẹ̀.
58. Wọ́n fi ojúbọ àwọn oriṣa wọn bí i ninu;wọ́n sì fi ère wọn mú un jowú.
59. Nígbà tí Ọlọrun gbọ́, inú bí i gidigidi;ó sì kọ Israẹli sílẹ̀ patapata.
60. Ó kọ ibùgbé rẹ̀ ní Ṣilo sílẹ̀,àní, àgọ́ rẹ̀ láàrin ọmọ eniyan.
61. Ó jẹ́ kí á gbé àmì agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn;ó sì fi ògo rẹ̀ lé ọ̀tá lọ́wọ́.
62. Ó jẹ́ kí á fi idà pa àwọn eniyan rẹ̀;ó sì bínú gidigidi sí àwọn eniyan ìní rẹ̀.
63. Iná run àwọn ọdọmọkunrin wọn;àwọn ọdọmọbinrin wọn kò sì rójú kọrin igbeyawo.
64. Àwọn alufaa kú ikú ogun;àwọn opó wọn kò sì rójú sọkún.
65. Lẹ́yìn náà, OLUWA dìde bí ẹni tají lójú oorun,bí ọkunrin alágbára tí ó mu ọtí yó tí ó ń kígbe.
66. Ó lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ sẹ́yìn;ó dójú tì wọ́n títí ayé.
67. Ó kọ àgọ́ àwọn ọmọ Josẹfu sílẹ̀;kò sì yan ẹ̀yà Efuraimu;
68. ṣugbọn ó yan ẹ̀yà Juda,ó sì yan òkè Sioni tí ó fẹ́ràn.
69. Níbẹ̀ ni ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀ tí ó ga bí ọ̀run sí,ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ bí ayé títí lae.
70. Ó yan Dafidi iranṣẹ rẹ̀;ó sì mú un láti inú agbo ẹran.
71. Ó mú un níbi tí ó ti ń tọ́jú àwọn aguntantí ó lọ́mọ lẹ́yìn,kí ó lè máa tọ́jú àwọn ọmọ Jakọbu, eniyan rẹ̀,àní àwọn ọmọ Israẹli, eniyan ìní rẹ̀.
72. Ó tọ́jú wọn pẹlu òdodo,ó sì tọ́ wọn pẹlu ìmọ̀.