Orin Dafidi 78:48-59 BIBELI MIMỌ (BM)

48. Ó fi yìnyín pa mààlúù wọn;ó sì sán ààrá pa agbo aguntan wọn.

49. Ó tú ibinu gbígbóná rẹ̀ lé wọn lórí:ìrúnú, ìkannú, ati ìpọ́njú,wọ́n dàbí ikọ̀ ìparun.

50. Ó fi àyè gba ibinu rẹ̀;kò dá ẹ̀mí wọn sí,ó sì fi àjàkálẹ̀ àrùn pa wọ́n.

51. O kọlu gbogbo àkọ́bí wọn ní ilẹ̀ Ijipti,àní, gbogbo àrẹ̀mọ ninu àgọ́ àwọn ọmọ Hamu.

52. Lẹ́yìn náà, ó kó àwọn eniyan rẹ̀ jáde bí agbo ẹranó sì dà wọ́n láàrin aṣálẹ̀ bí agbo aguntan.

53. Ó dà wọ́n lọ láìléwu, ẹ̀rù kò bà wọ́n;òkun sì bo àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀.

54. Ó kó wọn wá sí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀,sí orí òkè tí ó ti fi agbára rẹ̀ gbà.

55. Ó lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde kí wọn ó tó dé ibẹ̀;ó pín ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn bí ohun ìní;ó sì fi àwọn ọmọ Israẹli jókòó ninu àgọ́ wọn.

56. Sibẹ, wọ́n dán Ọ̀gá Ògo wò, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí i;wọn kò tẹ̀lé ìlànà rẹ̀.

57. Wọ́n yipada, wọ́n sì hu ìwà ọ̀dàlẹ̀bíi ti àwọn baba ńlá wọn;wọn kò ṣe é gbẹ́kẹ̀lé, wọ́n dàbí ọfà tí ó tẹ̀.

58. Wọ́n fi ojúbọ àwọn oriṣa wọn bí i ninu;wọ́n sì fi ère wọn mú un jowú.

59. Nígbà tí Ọlọrun gbọ́, inú bí i gidigidi;ó sì kọ Israẹli sílẹ̀ patapata.

Orin Dafidi 78