1. Nítòótọ́ Ọlọrun ṣeun fún Israẹli,ó ṣeun fún àwọn tí ọkàn wọn mọ́.
2. Ṣugbọn, ní tèmi, mo fẹ́rẹ̀ yọ̀ ṣubú,ẹsẹ̀ mi fẹ́rẹ̀ tàsé.
3. Nítorí mò ń ṣe ìlara àwọn onigbeeraganígbà tí mo rí ọrọ̀ àwọn eniyan burúkú.
4. Wọn kì í jẹ ìrora kankan,ara wọn dá pé, ó sì jọ̀lọ̀.
5. Wọn kì í ní wahala bí àwọn ẹlòmíràn;ìyọnu tíí dé bá àwọn ẹlòmíràn kì í dé ọ̀dọ̀ wọn.
6. Nítorí náà, wọn á kó ìgbéraga bọ ọrùn bí ẹ̀gbà,wọn á fi ìwà ipá bora bí aṣọ.
7. Wọ́n sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú wọn yíbò;èrò òmùgọ̀ sì kún ọkàn wọn ní àkúnwọ́sílẹ̀.
8. Wọ́n ń pẹ̀gàn eniyan, wọ́n ń sọ̀rọ̀ pẹlu ìlara;wọ́n sì ń fi ìgbéraga halẹ̀.