Orin Dafidi 72:8-13 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Kí ìjọba rẹ̀ ó lọ láti òkun dé òkun,ati láti odò ńlá títí dé òpin ayé.

9. Àwọn tí ń gbé aṣálẹ̀ yóo máa foríbalẹ̀ fún un;àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóo sì máa fi ẹnu gbo ilẹ̀ níwájú rẹ̀.

10. Àwọn ọba Taṣiṣi ati àwọn ọba erékùṣù gbogboyóo máa san ìṣákọ́lẹ̀ fún un;àwọn ọba Ṣeba ati ti Seba yóo máa mú ẹ̀bùn wá.

11. Gbogbo àwọn ọba yóo máa wólẹ̀ fún un;gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóo sì máa sìn ín.

12. Nítorí pé a máa gba talaka tí ó bá ké pè é sílẹ̀;a sì máa gba àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀,ati àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

13. A máa ṣíjú àánú wo àwọn aláìní ati talaka,a sì máa gba àwọn talaka sílẹ̀.

Orin Dafidi 72