Orin Dafidi 59:13-17 BIBELI MIMỌ (BM)

13. fi ibinu pa wọ́n run.Pa wọ́n run kí wọn má sí mọ́,kí àwọn eniyan lè mọ̀ pé Ọlọrun jọba lórí Jakọbu,ati títí dé òpin ayé.

14. Ní alaalẹ́ wọn á pada wáwọn á máa hu bí ajá, wọn á sì máa kiri ìlú.

15. Wọn á máa fẹsẹ̀ wọ́lẹ̀, wọn á máa wá oúnjẹ kiri,bí wọn ò bá sì yó wọn á máa kùn.

16. Ṣugbọn èmi ó kọrin ìyìn agbára rẹ;n óo kọrin sókè lówùúrọ̀, nípa ìfẹ́ rẹ tíkì í yẹ̀.Nítorí ìwọ ni o ti jẹ́ odi miìwọ sì ni ààbò mi nígbà ìpọ́njú.

17. Ọlọrun, agbára mi, n óo kọ orin ìyìn fún ọ,nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi,Ọlọrun tí ó ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn mí.

Orin Dafidi 59