Orin Dafidi 50:20-23 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Ẹ̀ ń jókòó sọ̀rọ̀ arakunrin yín níbi:ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ nípa ọmọ ìyá yín.

21. Gbogbo nǹkan wọnyi ni ẹ ti ṣe tí mo sì dákẹ́;ẹ wá ń rò ninu yín pé, èmi yín rí bákan náà.Ṣugbọn nisinsinyii mò ń ba yín wí,mo sì ń fi ẹ̀sùn kàn yín.

22. “Nítorí náà, ẹ fi èyí lékàn, ẹ̀yin tí ẹ gbàgbé Ọlọrun,kí n má baà fà yín ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kò sì ní sí ẹni tí yóo gbà yín kalẹ̀.

23. Ẹni tí ó bá mu ọpẹ́ wá, tí ó fi rúbọ sí mi, ni ó bu ọlá fún mi;ẹni tí ó bá sì rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ ni èmi Ọlọrun yóo gbà là.”

Orin Dafidi 50