Orin Dafidi 33:6-13 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run,èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.

7. Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì;ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.

8. Kí gbogbo ayé bẹ̀rù OLUWA,kí gbogbo aráyé dúró níwájú rẹ̀ pẹlu ọ̀wọ̀ ati ìbẹ̀rù!

9. Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà;ó pàṣẹ, ayé sì dúró.

10. OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán;ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.

11. Ètò OLUWA wà títí lae,èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

12. Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn,àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!

13. OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run,ó rí gbogbo eniyan;

Orin Dafidi 33