Orin Dafidi 33:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Nítorí ọ̀rọ̀ OLUWA dúró ṣinṣin;òtítọ́ sì ni ó fi ń ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.

5. OLUWA fẹ́ràn òdodo ati ẹ̀tọ́;ayé kún fún ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

6. Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run,èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.

7. Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì;ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.

Orin Dafidi 33