Orin Dafidi 22:2-7 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Ọlọrun mi, mo kígbe pè ọ́ lọ́sàn-án,ṣugbọn o ò dáhùn;mo kígbe lóru, n ò sì dákẹ́.

3. Sibẹ Ẹni Mímọ́ ni ọ́,o gúnwà, Israẹli sì ń yìn ọ́.

4. Ìwọ ni àwọn baba wa gbẹ́kẹ̀lé;wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọ, o sì gbà wọ́n.

5. Wọ́n kígbe pè ọ́, o sì gbà wọ́n;ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, ojú kò sì tì wọ́n.

6. Ṣugbọn kòkòrò lásán ni mí, n kì í ṣe eniyan;ayé kẹ́gàn mi, gbogbo eniyan sì ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà.

7. Gbogbo àwọn tí ó rí mi ní ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́;wọ́n ń yọ ṣùtì sí mi;wọ́n sì ń mi orí pé,

Orin Dafidi 22