Orin Dafidi 16:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Pa mí mọ́ Ọlọrun, nítorí ìwọ ni mo sá di.

2. Mo wí fún ọ, OLUWA, pé, “Ìwọ ni Oluwa mi;ìwọ nìkan ni orísun ire mi.”

3. Nípa àwọn eniyan mímọ́ tí ó wà nílẹ̀ yìí,wọ́n jẹ́ ọlọ́lá tí àwọn eniyan fẹ́ràn.

4. “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”

Orin Dafidi 16