Orin Dafidi 145:10-13 BIBELI MIMỌ (BM)

10. OLUWA, gbogbo ohun tí o dá ni yóo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ,àwọn eniyan mímọ́ rẹ yóo sì máa yìn ọ́.

11. Wọn óo máa ròyìn ògo ìjọba rẹ,wọn óo sì máa sọ nípa agbára rẹ,

12. láti mú àwọn eniyan mọ agbára rẹ,ati ẹwà ògo ìjọba rẹ.

13. Ìjọba ayérayé ni ìjọba rẹ,yóo sì máa wà láti ìran dé ìran.Olóòótọ́ ni OLUWA ninu gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀,olóore ọ̀fẹ́ sì ni ninu gbogbo ìṣe rẹ̀.

Orin Dafidi 145