14. Ó ní, “Ìhín ni ibi ìsinmi mi títí lae,níhìn-ín ni n óo máa gbé, nítorí pé ó wù mí.
15. N óo bù sí oúnjẹ rẹ̀ lọpọlọpọ;n óo fi oúnjẹ tẹ́ àwọn aláìní ibẹ̀ lọ́rùn.
16. N óo gbé ẹ̀wù ìgbàlà wọ àwọn alufaa rẹ̀,àwọn eniyan mímọ́ rẹ̀ yóo sì kọrin ayọ̀.
17. Níbẹ̀ ni n óo ti fún Dafidi ní agbára;mo ti gbé àtùpà kalẹ̀ fún ẹni tí mo fi òróró yàn.
18. N óo da ìtìjú bo àwọn ọ̀tá rẹ̀ bí aṣọ,ṣugbọn adé orí rẹ̀ yóo máa tàn yinrinyinrin.”