Orin Dafidi 132:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, ranti gbogbo ìyà tí Dafidi fara dà.

2. Ranti bí ó ṣe búra fún OLUWA,tí ó sì jẹ́jẹ̀ẹ́ fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu,

3. tí ó ní, “N kò ní wọ inú ilé mi,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní bọ́ sí orí ibùsùn mi;

4. n kò ní sùn,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní tòògbé,

5. títí tí n óo fi wá ààyè fún OLUWA,àní, tí n óo fi pèsè ibùgbé fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu.”

6. A gbúròó rẹ̀ ní Efurata,a rí i ní oko Jearimu.

7. “Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ibùgbé rẹ̀;ẹ jẹ́ kí á lọ wólẹ̀ níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.”

8. Dìde, OLUWA, lọ sí ibi ìsinmi rẹ,tìwọ ti àpótí agbára rẹ.

9. Jẹ́ kí àwọn alufaa rẹ wọ ẹ̀wù òdodo,kí àwọn eniyan mímọ́ rẹ sì máa kọrin ayọ̀.

10. Nítorí ti Dafidi, iranṣẹ rẹ,má jẹ́ kí ẹni tí a fi òróró rẹ yàn yíjú kúrò lára rẹ.

11. OLUWA ti ṣe ìbúra tí ó dájú fún Dafidi,èyí tí kò ní yipada; ó ní,“Ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹni n óo gbé ka orí ìtẹ́ rẹ.

Orin Dafidi 132