Orin Dafidi 107:13-17 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn,ó sì gbà wọ́n ninu ìṣẹ́ wọn.

14. Ó yọ wọ́n kúrò ninu òkùnkùn ati ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn,ó sì já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn.

15. Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,àní nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún eniyan.

16. Nítorí pé ó fọ́ ìlẹ̀kùn idẹ,ó sì gé ọ̀pá ìdábùú irin ní àgéjá.

17. Àwọn kan ninu wọn di òmùgọ̀nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,ojú sì pọ́n wọn nítorí àìdára wọn.

Orin Dafidi 107