Orin Dafidi 105:5-24 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ẹ ranti iṣẹ́ ribiribi tí ó ti ṣe,ẹ ranti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ati ìdájọ́ rẹ̀.

6. Ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.

7. OLUWA ni Ọlọrun wa,ìdájọ́ rẹ̀ kárí gbogbo ayé.

8. Títí lae ni ó ń ranti majẹmu rẹ̀,ó ranti àṣẹ tí ó pa fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,

9. majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó fi ìbúra ṣe fún Isaaki,

10. tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí òfin,àní fún Israẹli gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ayérayé,

11. ó ní: “Ẹ̀yin ni n óo fi ilẹ̀ Kenaani fún,yóo jẹ́ ìpín yín tí ẹ óo jogún.”

12. Nígbà tí wọ́n kéré ní iye,tí wọn kò tíì pọ̀ rárá, tí wọn sì jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ náà,

13. tí wọn ń káàkiri láti orílẹ̀-èdè dé orílẹ̀-èdè,láti ìjọba kan dé òmíràn,

14. kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ni wọ́n lára,ó bá àwọn ọba wí nítorí wọn.

15. Ó ní, “Ẹ kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ẹni àmìòróró mi,ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe àwọn wolii mi níbi.”

16. Nígbà kan, ó mú kí ìyàn jà ní ilẹ̀ náà:ó ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ mọ́ wọn lẹ́nu.

17. Ṣugbọn ó kọ́ rán ọkunrin kan ṣáájú wọn,Josẹfu, ẹni tí a tà lẹ́rú.

18. Wọ́n so ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ mọ́ ọn lẹ́sẹ̀,wọ́n ti ọrùn rẹ̀ bọ irin,

19. títí ìgbà tí ohun tí ó sọ fi ṣẹ,tí OLUWA sì jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

20. Ọba ranṣẹ pé kí wọ́n tú u sílẹ̀,aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè sì dá a sílẹ̀.

21. Ó fi jẹ aláṣẹ ilé rẹ̀,ati alákòóso gbogbo nǹkan ìní rẹ̀;

22. láti máa ṣe olórí àwọn ìjòyè rẹ̀,kí ó sì máa kọ́ àwọn àgbà ìlú ní ìmọ̀.

23. Lẹ́yìn náà, Israẹli dé sí Ijipti,Jakọbu ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Hamu.

24. OLUWA mú kí àwọn eniyan rẹ̀ pọ̀ sí i,ó sì mú kí wọ́n lágbára ju àwọn ọ̀tá wọn lọ.

Orin Dafidi 105