Orin Dafidi 105:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, ẹ pe orúkọ rẹ̀,ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè.

2. Ẹ kọrin sí i, ẹ kọ orin ìyìn sí i,ẹ sọ nípa gbogbo iṣẹ́ ribiribi rẹ̀.

3. Ẹ máa fi orúkọ mímọ́ rẹ̀ yangàn,kí ọkàn àwọn tí ń wá OLUWA ó máa yọ̀.

4. Ẹ wá ojurere OLUWA ati agbára rẹ̀,ẹ máa wá ojurere rẹ̀ nígbà gbogbo.

Orin Dafidi 105