Orin Dafidi 104:9-16 BIBELI MIMỌ (BM)

9. O ti pa ààlà tí wọn kò gbọdọ̀ kọjá,kí wọn má baà tún bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.

10. Ìwọ ni o mú kí àwọn orísun máa tú omi jáde ní àfonífojì;omi wọn sì ń ṣàn láàrin àwọn òkè.

11. Ninu omi wọn ni gbogbo ẹranko tí ń mu,ibẹ̀ sì ni àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń rẹ òùngbẹ.

12. Lẹ́bàá orísun wọnyini àwọn ẹyẹ ń gbé,wọ́n sì ń kọrin lórí igi.

13. Láti ibùgbé rẹ lókè ni o tí ń bomi rin àwọn òkè ńlá.Ilẹ̀ sì mu àmutẹ́rùn nípa iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

14. Ó ń mú kí koríko dàgbà fún àwọn ẹran láti jẹ,ati ohun ọ̀gbìn fún ìlò eniyan,kí ó lè máa mú oúnjẹ jáde láti inú ilẹ̀;

15. ati ọtí waini tí ń mú inú eniyan dùn,ati epo tí ń mú ojú eniyan dán,ati oúnjẹ tí ń fún ara lókun.

16. Àwọn igi OLUWA ń mu omi ní àmutẹ́rùn,àní àwọn igi kedari Lẹbanoni tí ó gbìn.

Orin Dafidi 104