Orin Dafidi 104:3-11 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ìwọ tí o tẹ́ àjà ibùgbé rẹ sórí omi,tí o fi ìkùukùu ṣe kẹ̀kẹ́ ogun rẹ,tí o sì ń lọ geere lórí afẹ́fẹ́.

4. Ìwọ tí o fi ẹ̀fúùfù ṣe iranṣẹ,tí o sì fi iná ati ahọ́n iná ṣe òjíṣẹ́ rẹ.

5. Ìwọ tí o gbé ayé kalẹ̀ lórí ìpìlẹ̀ rẹ̀,tí kò sì le yẹ̀ laelae.

6. O fi ibú omi bò ó bí aṣọ,omi sì borí àwọn òkè ńlá.

7. Nígbà tí o bá wọn wí, wọ́n sá,nígbà tí o sán ààrá, wọ́n sá sẹ́yìn.

8. Wọ́n ṣàn kọjá lórí òkèlọ sí inú àfonífojì,sí ibi tí o yàn fún wọn.

9. O ti pa ààlà tí wọn kò gbọdọ̀ kọjá,kí wọn má baà tún bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.

10. Ìwọ ni o mú kí àwọn orísun máa tú omi jáde ní àfonífojì;omi wọn sì ń ṣàn láàrin àwọn òkè.

11. Ninu omi wọn ni gbogbo ẹranko tí ń mu,ibẹ̀ sì ni àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń rẹ òùngbẹ.

Orin Dafidi 104