Orin Dafidi 102:8-16 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Àwọn ọ̀tá ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru,àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi ń fi orúkọ mi ṣépè.

9. Mò ń jẹ eérú bí oúnjẹ,mo sì ń mu omijé mọ́ omi

10. nítorí ìrúnú ati ibinu rẹ;o gbé mi sókè,o sì jù mí nù.

11. Ọjọ́ ayé mi ń lọ bí òjìji àṣáálẹ́,mo sì ń rọ bíi koríko.

12. Bẹ́ẹ̀ sì ni ìwọ OLUWA gúnwà títí lae,ọlá rẹ sì wà láti ìran dé ìran.

13. Ìwọ óo dìde, o óo sì ṣàánú Sioni,nítorí ó tó àkókò láti fi ojú àánú wò ó.Àkókò tí o dá tó.

14. Nítorí àwọn òkúta rẹ̀ ṣe iyebíye lójú àwọn iranṣẹ rẹ,àánú rẹ̀ sì ṣeni bí ó tilẹ̀ ti wó dà sinu erùpẹ̀.

15. Àwọn orílẹ̀-èdè yóo máa bẹ̀rù orúkọ OLUWA,gbogbo ọba ayé ni yóo sì máa bẹ̀rù ògo rẹ̀.

16. Nítorí OLUWA yóo tún Sioni kọ́,yóo sì fara hàn ninu ògo rẹ̀.

Orin Dafidi 102