Nọmba 24:15-18 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi òwe sọ̀rọ̀, pé,“Ọ̀rọ̀ Balaamu ọmọ Beori nìyí,ọ̀rọ̀ ẹni tí ó ríran dájúdájú.

16. Ìran ẹni tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọrun,tí ó ní ìmọ̀ ẹni tí ó ga jùlọ,tí ó sì ń rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olodumare.Nítòótọ́ ó ṣubú, ṣugbọn ojú rẹ̀ kò wà ní dídì.

17. Mo wo ọjọ́ iwájú rẹ,mo sì rí ẹ̀yìn ọ̀la rẹ.Ìràwọ̀ kan yóo jáde wá láàrin àwọn ọmọ Jakọbu,ọ̀pá àṣẹ yóo ti ààrin àwọn ọmọ Israẹli jáde wá;yóo run àwọn àgbààgbà Moabu,yóo sì wó àwọn ará Seti palẹ̀.

18. Yóo ṣẹgun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ní Edomu,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Yóo ṣẹgun àwọn ará Seiri tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá wọn,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Israẹli yóo sì máa pọ̀ sí i ní agbára.

Nọmba 24