Nahumu 1:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọ̀rọ̀ OLUWA nìyí; tí a kọ sinu ìwé ìran tí Nahumu ará Elikoṣi rí nípa ìlú Ninefe.

2. OLUWA tíí jowú tíí sìí máa gbẹ̀san ni Ọlọrun.OLUWA a máa gbẹ̀san, a sì máa bínú.OLUWA a máa gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,a sì máa fi ìrúnú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ọ̀tá rẹ̀.

3. OLUWA kì í tètè bínú;ó lágbára lọpọlọpọ,kì í sìí dá ẹni tí ó bá jẹ̀bi láre.Ipa ọ̀nà rẹ̀ wà ninu ìjì ati ẹ̀fúùfù líle,awọsanma sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4. Ó bá òkun wí, ó mú kí ó gbẹ,ó sì mú kí gbogbo odò gbẹ pẹlu;koríko ilẹ̀ Baṣani ati ti òkè Kamẹli gbẹ,òdòdó ilẹ̀ Lẹbanoni sì rẹ̀.

5. Àwọn òkè ńláńlá mì tìtì níwájú rẹ̀,àwọn òkè kéékèèké sì yọ́.Ilẹ̀ di asán níwájú rẹ̀,ayé ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀ di òfo.

Nahumu 1