5. Àwọn ará Jebusi sọ fún Dafidi pé, “O ò ní wọ ìlú yìí.” Ṣugbọn Dafidi ṣẹgun ibi ààbò Sioni, tí à ń pè ní ìlú Dafidi.
6. Dafidi ní, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ́kọ́ pa ará Jebusi kan ni yóo jẹ́ balogun fún àwọn ọmọ ogun mi.” Joabu, ọmọ Seruaya ni ó kọ́kọ́ lọ, ó sì di balogun.
7. Dafidi lọ ń gbé ibi ààbò náà, nítorí náà ni wọ́n ṣe ń pe ibẹ̀ ní ìlú Dafidi.
8. Ó tún ìlú náà kọ́ yípo, bẹ̀rẹ̀ láti Milo, ibi tí a ti kun ilẹ̀ náà yíká. Joabu sì parí èyí tí ó kù.
9. Dafidi bẹ̀rẹ̀ sí di alágbára sí i, nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun wà pẹlu rẹ̀.