Kronika Kinni 11:24-39 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Àwọn ohun tí Bẹnaya, ọmọ Jehoiada, ṣe nìyí, tí ó sọ ọ́ di olókìkí, yàtọ̀ sí ti àwọn akọni mẹta tí a sọ nípa wọn.

25. Ó di olókìkí láàrin àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun; ṣugbọn òkìkí tirẹ̀ kò tó ti àwọn akọni mẹta náà. Dafidi bá fi ṣe olórí àwọn tí ń ṣọ́ ọba.

26. Àwọn olókìkí mìíràn ninu àwọn ọmọ ogun Dafidi nìwọ̀nyí: Asaheli, arakunrin Joabu; ati Elihanani, ọmọ Dodo, ará Bẹtilẹhẹmu;

27. Ṣamotu, láti Harodu;

28. Helesi, láti inú ìdílé Peloni, Ira, ọmọ Ikeṣi ará Tekoa, ati Abieseri, láti Anatoti

29. Sibekai, láti inú ìdílé Huṣati, ati Ilai, láti inú ìdílé Aho;

30. Maharai, ará Netofa, ati Helodi, ọmọ Baana, ará Netofa;

31. Itai, ọmọ Ribai, ará Gibea, láti inú ẹ̀yà Bẹnjamini, ati Bẹnaya, ará Piratoni;

32. Hurai, ará etí odò Gaaṣi, ati Abieli, ará Aribati;

33. Asimafeti, ará Bahurumu, ati Eliaba ará Ṣaaliboni;

34. Haṣemu, ará Gisoni, ati Jonatani, ọmọ Ṣagee, ará Harari;

35. Ahiamu, ọmọ Sakari, ará Harari, ati Elifali, ọmọ Uri;

36. Heferi, ará Mekerati, ati Ahija, ará Peloni;

37. Hesiro, ará Kamẹli, ati Naarai ọmọ Esibai;

38. Joẹli, arakunrin Natani, ati Mibihari, ọmọ Hagiri,

39. Seleki, ará Amoni, ati Naharai, ará Beeroti, tí ń ru ihamọra Joabu ọmọ Seruaya.

Kronika Kinni 11