Joẹli 2:4-9 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ìrísí wọn dàbí ìrísí ẹṣin,wọ́n sì ń sáré bí ẹṣin tí ń lọ ojú ogun.

5. Ìró wọn dàbí ìró kẹ̀kẹ́ ogun,wọ́n ń bẹ́ lórí àwọn òkè ńlá.Ìró wọn dàbí ìró iná tí ń jó pápá,bí ìgbà tí àwọn alágbára ọmọ ogun múra fún ogun.

6. Ìdààmú bá àwọn orílẹ̀-èdè tí ó bá ti fojú kàn wọ́n,gbogbo ọkàn á rẹ̀wẹ̀sì.

7. Wọ́n ń sáré bí akọni,wọ́n ń fo ògiri bí ọmọ ogun.Wọ́n tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́,ẹnikẹ́ni kò sì yà kúrò ní ọ̀nà tirẹ̀.

8. Wọn kò fi ara gbún ara wọn,olukuluku ń lọ ní ọ̀nà tirẹ̀;wọ́n kọlu àwọn nǹkan ààbò láìní ìdádúró.

9. Wọ́n ń gun odi ìlú,wọ́n ń sáré lórí odi.Wọ́n ń gun orí ilé wọlé,wọ́n gba ojú fèrèsé bẹ́ sinu ọ̀dẹ̀dẹ̀ bí olè.

Joẹli 2