Jeremaya 48:25-34 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Ipá Moabu ti pin, a sì ti ṣẹ́ ẹ lápá. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

26. OLUWA ní,“Ẹ rọ Moabu lọ́tí yó,nítorí pé ó gbéraga sí OLUWA;kí ó lè máa yíràá ninu èébì rẹ̀,a óo sì fi òun náà ṣẹ̀sín.

27. Moabu, ṣebí ò ń fi Israẹli ṣe yẹ̀yẹ́?Ṣé o bá a láàrin àwọn ọlọ́ṣà ni,tí ó fi jẹ́ pé nígbàkúùgbà tí o bá ń sọ̀rọ̀ rẹ̀, ń ṣe ni o máa ń mi orí rẹ?

28. “Ẹ fi ààrin ìlú sílẹ̀, kí ẹ lọ máa gbé inú àpáta, ẹ̀yin ará Moabu!Ẹ ṣe bí àdàbà, tí ó kọ́lé rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ ẹnu ihò àpáta.

29. A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu,ó ní ìgbéraga lọpọlọpọ,a ti gbọ́ nípa èrò gíga rẹ̀, ati ìgbéraga rẹ̀,nípa àfojúdi rẹ̀, ati nípa ìwà ìjọra-ẹni-lójú rẹ̀.

30. Mo mọ̀ pé aláfojúdi ni.Ó ń fọ́nnu lásán ni, kò lè ṣe nǹkankan tó yanjú.

31. Nítorí náà, ni mo ṣe ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, tí mò ń kígbe sókè nítorí Moabutí mo sì ń ṣọ̀fọ̀ nítorí àwọn ará Kiri Heresi.

32. Ìwọ ọgbà àjàrà Sibima,ọ̀rọ̀ rẹ pa mí lẹ́kún, ju ti Jaseri lọ!Àwọn ẹ̀ka rẹ tàn dé òkun, wọ́n tàn títí dé Jaseri,apanirun sì ti kọlu àwọn èso ẹ̀ẹ̀rùn rẹ, ati èso àjàrà rẹ.

33. Wọ́n ti mú ayọ̀ ati ìdùnnú kúrò ní ilẹ̀ ọlọ́ràá Moabu;mo ti mú kí ọtí waini tán níbi tí wọ́n ti ń ṣe é,kò sí ẹni tí ó ń ṣe ọtí waini pẹlu ariwo ayọ̀ mọ́, ariwo tí wọn ń pa kì í ṣe ti ayọ̀.

34. “Heṣiboni ati Eleale kígbe sókè, igbe wọn sì dé Jahasi láti Soari, ó dé Horonaimu ati Egilati Ṣeliṣiya. Àwọn odò Nimrimu pàápàá ti gbẹ.

Jeremaya 48