Ẹkún Jeremaya 4:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Wo bí wúrà ti dọ̀tí,tí ojúlówó wúrà sì yipada;tí àwọn òkúta Tẹmpili mímọ́ sì fọ́nká ní gbogbo ìkóríta.

2. Ẹ wo àwọn ọdọmọkunrin Sioni,àwọn ọmọ tí wọn níye lórí bí ojúlówó wúrà,tí a wá ń ṣe bí ìkòkò amọ̀;àní, bí ìkòkò amọ̀ lásánlàsàn.

3. Àwọn ajáko a máa fún àwọn ọmọ wọn lọ́mú.Ṣugbọn àwọn eniyan mi ti di ìkà,bí ògòǹgò inú aṣálẹ̀.

4. Ahọ́n ọmọ ọmú lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu rẹ̀ nítorí òùngbẹ.Àwọn ọmọde ń tọrọ oúnjẹ,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó fún wọn.

5. Àwọn tí wọn tí ń jẹ oúnjẹ àdídùndi ẹni tí ń ṣa ilẹ̀ jẹ kiri ní ìgboro.Àwọn tí wọn tí ń fi aṣọ àlàárì boradi ẹni tí ń sùn lórí òkítì eérú.

6. Ìjìyà àwọn eniyan mi pọ̀ ju ti àwọn ará Sodomu lọ,Sodomu tí ó parun lójijì,láìjẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn án.

Ẹkún Jeremaya 4