Àwọn Ọba Kinni 18:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, ní ọdún kẹta tí ọ̀dá ti dá, OLUWA sọ fún Elija pé, “Lọ fi ara rẹ han Ahabu ọba, n óo sì rọ̀jò sórí ilẹ̀.”

2. Elija bá lọ fi ara han Ahabu.Ìyàn tí ó mú ní ìlú Samaria pọ̀ pupọ.

3. Ahabu pe Ọbadaya, tí ó jẹ́ alabojuto ààfin. Ọbadaya jẹ́ ẹni tí ó bẹ̀rù OLUWA gan-an.

4. Nígbà tí Jesebẹli bẹ̀rẹ̀ sí pa àwọn wolii OLUWA, Ọbadaya yìí ló kó ọgọrun-un ninu wọn pamọ́ sinu ihò àpáta meji, ó kó aadọta sinu ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì ń fún wọn ní oúnjẹ ati omi.

5. Ahabu sọ fún Ọbadaya pé, “Lọ wo gbogbo orísun omi ati àfonífojì ní gbogbo ilẹ̀ yìí, kí o wò ó bóyá a lè rí koríko láti fi bọ́ àwọn ẹṣin ati àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, kí wọ́n má baà kú.”

Àwọn Ọba Kinni 18