10. Ọdún mọkanlelogoji ni ó fi jọba ní Jerusalẹmu. Maaka ọmọ Absalomu ni ìyá baba rẹ̀.
11. Asa ṣe ohun tí ó dára lójú OLUWA gẹ́gẹ́ bíi Dafidi baba ńlá rẹ̀.
12. Gbogbo àwọn aṣẹ́wó ọkunrin tí wọ́n wà ní ojúbọ àwọn oriṣa káàkiri ní ilẹ̀ Juda, ni Asa lé jáde kúrò ni ilẹ̀ náà; ó sì kó gbogbo àwọn oriṣa tí àwọn baba ńlá rẹ̀ ti ṣe dànù.
13. Ó yọ Maaka, ìyá baba rẹ̀, kúrò lórí oyè ìyá ọba, nítorí pé Maaka yá ère tí ó tini lójú kan fún oriṣa Aṣera. Asa gé oriṣa náà lulẹ̀, ó sì dáná sun ún ní àfonífojì Kidironi.