Máàkù 15:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, àwọn olórí àlùfáà, àwọn àgbààgbà, àwọn alùkọ́ òfin àti gbogbo àjọ ìgbìmọ̀ fi ẹnu kò lórí ohun tí wọn yóò ṣe. Wọ́n sì de Jésù, wọ́n mú un lọ, wọ́n sì fi lé Pílátù lọ́wọ́.

2. Pílátù sì bi í léèrè, ó ni, “Ṣe ìwọ ni ọba àwọn Júù?”Jésù sì dáhùn pé, “Ìwọ wí.”

3. Àwọn olórí àlùfáà fi ẹ̀sùn ohun púpọ̀ kàn án.

4. Pílátù sì tún bi í léèrè pé, “Ṣe ìwọ kò dáhùn ni? Wo gbogbo ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn ọ.”

5. Ṣùgbọ́n Jésù kò da lohùn síbẹ̀, tóbẹ́ẹ̀ ti ẹnu fi ya Pílátù.

6. Ní báyìí, nígbà àjọ, gẹ́gẹ́ bí àsà, òun a máa dá òǹdè kan sílẹ̀ fún àwọn, ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá béèrè fún.

7. Ọkùnrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Bárábà. Wọ́n ti ju òun àti àwọn ọlọ̀tẹ̀ ẹgbẹ́ rẹ̀ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n, nítorí wọ́n sọ̀tẹ̀ sí ìjọba, wọ́n sì pa ènìyàn nínú ìdìtẹ̀ wọn.

8. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì lọ bá Pílátù, wọ́n ní kí ó ṣe bí ó ti máa ń ṣe fún wọn ní ọdọọdún.

9. Pílátù béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Ṣe ẹ̀yín ń fẹ́ kí èmi dá ọba àwọn Júù sílẹ̀ fún yin?”

Máàkù 15