11. “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbéàgọ́ Dáfídì tí ó wó róÈmi yóò mọ odi rẹ̀ tí ó wóÈmi yóò sì sọ ahoro rẹ̀ di ìlúÈmi yóò sì kọ bí ó ti wà tẹ́lẹ̀
12. kí wọn le jógun ìyókù Édómùàti gbogbo orílẹ̀ èdè ti ń jẹ́ orúkọ mi,”ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
13. “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,“Tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè báTí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn báÀwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀Tí yóò sì ṣàn láti ara àwọn òkè kékèké.
14. Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Ísírẹ́lì ènìyàn mi padà bọ̀Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọnWọn yóò sì gbin àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọnwọn yóò sì se ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn
15. Èmi yóò gbin Ísírẹ́lì sí orí ilẹ̀ rẹ̀.A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláékúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.