Num 31:24-33 Yorùbá Bibeli (YCE)

24. Ki ẹnyin ki o si fọ̀ aṣọ nyin ni ijọ́ keje, ẹnyin o si di mimọ́, lẹhin eyinì li ẹnyin o si wá sinu ibudó.

25. OLUWA si sọ fun Mose pe,

26. Kà iye ikogun ti a kó, ti enia ati ti ẹran, iwọ ati Eleasari alufa, ati awọn olori ile baba ijọ:

27. Ki o si pín ikogun na si ipa meji; lãrin awọn ologun, ti o jade lọ si ogun na, ati lãrin gbogbo ijọ.

28. Ki o si gbà ohun idá ti OLUWA lọwọ awọn ologun ti nwọn jade lọ si ogun na: ọkan ninu ẹdẹgbẹta, ninu awọn enia, ati ninu malu, ati ninu kẹtẹkẹtẹ, ati ninu agbo-ẹran:

29. Gbà a ninu àbọ ti wọn, ki o si fi i fun Eleasari alufa, fun ẹbọ igbesọsoke OLUWA.

30. Ati ninu àbọ ti iṣe ti awọn ọmọ Israeli, ki iwọ ki o si gbà ipín kan ninu ãdọta, ninu enia, ninu malu, ninu kẹtẹkẹtẹ, ati ninu agbo-ẹran, ninu onirũru ẹran, ki o si fi wọn fun awọn ọmọ Lefi, ti nṣe itọju agọ́ OLUWA.

31. Ati Mose ati Eleasari alufa si ṣe bi OLUWA ti paṣẹ fun Mose.

32. Ati ikogun ti o kù ninu ohun-iní ti awọn ologun kó, o jẹ́ ọkẹ mẹrinlelọgbọ̀n o din ẹgbẹdọgbọ̀n agutan,

33. Ẹgba mẹrindilogoji malu,

Num 31