Isa 10:3-16 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. Kili ẹnyin o ṣe lọjọ ibẹ̀wo, ati ni idahoro ti yio ti okere wá? tali ẹnyin o sá tọ̀ fun irànlọwọ? nibo li ẹnyin o si fi ogo nyin si?

4. Laisi emi nwọn o tẹ̀ ba labẹ awọn ara-tubu, nwọn o si ṣubu labẹ awọn ti a pa. Ni gbogbo eyi ibinu rẹ̀ kò yi kuro, ṣugbọn ọwọ́ rẹ̀ nà jade sibẹ.

5. Egbe ni fun Assuri, ọgọ ibinu mi, ati ọ̀pa ọwọ́ wọn ni irúnu mi.

6. Emi o ran a si orilẹ-ède agabàgebe, ati fun awọn enia ibinu mi li emi o paṣẹ kan, lati ko ikogun, ati lati mu ohun ọdẹ, ati lati tẹ̀ wọn mọlẹ bi ẹrẹ̀ ni igboro.

7. Ṣugbọn on kò rò bẹ̃, bẹ̃ni ọkàn rẹ̀ kò rò bẹ̃; ṣugbọn o wà li ọkàn rẹ̀ lati parun ati lati ke orilẹ-ède kuro, ki iṣe diẹ.

8. Nitori o wipe, Ọba kọ awọn ọmọ-alade mi ha jẹ patapata?

9. Kalno kò ha dabi Karkemiṣi? Hamati kò ha dabi Arpadi? Samaria kò ha dabi Damasku?

10. Gẹgẹ bi ọwọ́ mi ti nà de ijọba ere ri, ere eyi ti o jù ti Jerusalemu ati ti Samaria lọ.

11. Bi emi ti ṣe si Samaria ati ere rẹ̀, emi kì yio ha ṣe bẹ̃ si Jerusalemu ati ere rẹ̀ bi?

12. Nitorina yio si ṣe, nigbati Oluwa ti ṣe gbogbo iṣẹ rẹ̀ lori òke Sioni ati Jerusalemu, emi o ba eso aiya lile ọba Assiria wi, ati ogo ìwo giga rẹ̀.

13. Nitori o wipe, nipa agbara ọwọ́ mi ni emi ti ṣe e, ati nipa ọgbọ́n mi; nitori emi moye, emi si ti mu àla awọn enia kuro, emi si ti ji iṣura wọn, emi si ti sọ awọn ará ilu na kalẹ bi alagbara ọkunrin.

14. Ọwọ́ mi si ti wá ọrọ̀ awọn enia ri bi itẹ ẹiyẹ: ati gẹgẹ bi ẹnipe ẹnikan nko ẹyin ti o kù, li emi ti kó gbogbo aiye jọ; kò si ẹniti o gbọ̀n iyẹ, tabi ti o ya ẹnu, tabi ti o dún.

15. Ãke ha le fọnnu si ẹniti nfi i la igi? tabi ayùn ha le gbe ara rẹ̀ ga si ẹniti nmì i? bi ẹnipe ọgọ le mì ara rẹ̀ si awọn ti o gbe e soke, tabi bi ẹnipe ọpa le gbe ara rẹ̀ soke, bi ẹnipe ki iṣe igi.

16. Nitorina ni Oluwa, Oluwa awọn ọmọ-ogun yio mu awọn tirẹ̀ ti o sanra di rirù: ati labẹ ogo rẹ̀ yio da jijo kan bi jijo iná.

Isa 10